Oba Kehinde Gbadewole Olugbenle, Olu ti Ilẹ̀ Ilaro, Gúúsù Ìwọ̀ Oòrùn Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, mọrírì ìrànlọ́wọ́ ẹ̀kọ́ tó ga láti ọ̀dọ̀ ìjọ Mùsùlùmí Ahmadiyya ní Nàìjíríà.
Nígbà tó ń sọ̀rọ̀ níbi ìpàdé ẹ̀sìn Islam ọgọ́ta ọdún ti Ìjọ Mùsùlùmí Ahmadiyya gbe kálẹ̀ ní Orílẹ̀-èdè Gẹ̀ẹ́sì, ní Hadeeqatul Mahdi, Alton Hamshire, London.

Oba Olugbenle tó darí àwọn olóyè àti àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà mìíràn láti agbègbè rẹ̀ sí ìpàdé náà mọrírì ìdásílẹ̀ Yunifásítì Ahmadiyya àkọ́kọ́ kárí ayé ní Ikirun, Ìpínlẹ̀ Osun àti Ilé-ẹ̀kọ́ Ìmọ̀-ẹ̀rọ Masroor International ní Ilaro, Ìpínlẹ̀ Ogun ní ìwọ̀-oòrùn gúúsù Nàìjíríà bakanna, gẹ́gẹ́ bí ìfihàn àti ìfarajìn tí ìjọ Islam fún ìdàgbàsókè ènìyàn àti ìdàgbàsókè ẹ̀kọ́ ní Nàìjíríà.
Ó sọ ọ̀rọ̀ yìí nígbà ìpàdé ọ̀sán ti ìjọ Mùsùlùmí náà ní ọjọ́ Sátidé gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan lára àwọn àlejò olùbánisọ̀rọ̀.
